Bíbélì Ló Kọ́kọ́ Sọ Ọ́
● “A kì í ṣàdédé bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò, bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ ní kánjúkánjú. A kì í fìkánjú béèrè ìbéèrè, bó ti wù kí ìbéèrè ọ̀hún ṣe pàtàkì tó, a kì í sì í fagbára múni dáhùn. Ìdánudúró díẹ̀ tí ń fúnni láyè láti ronú ni ọ̀nà tí ojúlówó ọmọlúwàbí gbà ń bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò tó sì fi ń bá a nìṣó. Dídákẹ́ nítumọ̀ lójú àwọn ẹ̀yà Lakota . . . Wọ́n máa ń ṣe [èyí] gẹ́gẹ́ bí ojúlówó ìwà ìbọ̀wọ̀fúnni àti títẹ̀lé ìlànà náà tó sọ pé, ‘ńṣe la máa ń ronú ká tó sọ̀rọ̀.’”—Luther Standing Bear, olóye Oglala ti ẹ̀yà Sioux, (nǹkan bí 1868 sí 1939).
“Kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́ ọ̀wọ́n. Kí olúkúlùkù ènìyàn yára nípa ọ̀rọ̀ gbígbọ́, lọ́ra nípa ọ̀rọ̀ sísọ, lọ́ra nípa ìrunú.”—Jákọ́bù 1:19, Bíbélì (ọ̀rúndún kìíní Sànmánì Tiwa).
“Ọkàn-àyà olódodo máa ń ṣe àṣàrò láti lè dáhùn, ṣùgbọ́n ẹnu àwọn ẹni burúkú máa ń tú àwọn ohun búburú jáde.”—Òwe 15:28, Bíbélì (nǹkan bí ọ̀rúndún kẹjọ ṣááju Sànmánì Tiwa).
“Gbogbo ẹ̀mí rẹ̀ ni arìndìn ń tú jáde, ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́n a máa mú kí ó pa rọ́rọ́ títí dé ìkẹyìn.”—Òwe 29:11, Bíbélì (nǹkan bí ọ̀rúndún kẹjọ ṣááju Sànmánì Tiwa).
[Àwòrán Credit Line tó wà ní ojú ìwé 15]
Fọ́tò látọwọ́ David Barry, ti Denver Public Library, Western History Collection