Thursday, April 16
Mo ké pe Jèhófà nínú wàhálà mi, igbe tí mo ké sọ́dọ̀ rẹ̀ fún ìrànlọ́wọ́ sì dé etí rẹ̀.—Sm. 18:6.
Ọba Dáfídì mọ Jèhófà, ó sì gbẹ́kẹ̀ lé e. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí Ọba Sọ́ọ̀lù àtàwọn míì fẹ́ pa á, Dáfídì gbàdúrà sí Jèhófà pé kó ran òun lọ́wọ́. Jèhófà gbọ́ àdúrà ẹ̀, ó sì ràn án lọ́wọ́. Lẹ́yìn náà, Dáfídì sọ pé: “Jèhófà wà láàyè!” (Sm. 18:46) Kí ni Dáfídì ń sọ nígbà tó sọ ọ̀rọ̀ yẹn? Ìwé kan tó ń ṣàlàyé Bíbélì sọ pé ọ̀rọ̀ tí Dáfídì sọ yìí fi hàn pé ó dá a lójú pé Jèhófà jẹ́ “Ọlọ́run alààyè tó máa ń gba àwọn èèyàn ẹ̀ sílẹ̀ ní gbogbo ìgbà.” Bí Jèhófà ṣe gba Dáfídì sílẹ̀ láwọn ìgbà tó níṣòro jẹ́ kó dá a lójú pé Ọlọ́run wà lóòótọ́, ìyẹn jẹ́ kó pinnu pé Jèhófà lòun á máa sìn, òun á sì máa yìn ín. (Sm. 18:28, 29, 49) Tó bá dá wa lójú pé Ọlọ́run alààyè ni Jèhófà, àá máa fìtara sìn ín. Yàtọ̀ síyẹn, á jẹ́ ká máa fara da àwọn ìṣòro wa, á sì tún jẹ́ kó máa wù wá láti ṣiṣẹ́ kára lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn rẹ̀. Paríparí ẹ̀, kò ní jẹ́ ká fi Jèhófà sílẹ̀. w24.06 20-21 ¶3-4
Friday, April 17
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnì kankan kó yín ṣìnà lọ́nàkọnà.—2 Tẹs. 2:3.
Kí la lè kọ́ nínú ọ̀rọ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ sáwọn ará Tẹsalóníkà? Tá a bá gbọ́ ọ̀rọ̀ kan tó ta ko ohun tá a ti kọ́ nínú Bíbélì tàbí tá a gbọ́ ìròyìn tó ń dẹ́rù bani, ó yẹ ká wádìí ẹ̀ wò ká tó gbà á gbọ́. Nígbà ìjọba Soviet Union, àwọn ọ̀tá ètò Ọlọ́run kọ lẹ́tà kan tó jọ pé oríléeṣẹ́ ló ti wá, wọ́n sì pín in kiri. Lẹ́tà yẹn sọ pé kí àwọn arákùnrin kan dá ètò kan sílẹ̀ tí kì í ṣe ara ètò Ọlọ́run. Ẹni tó bá ka lẹ́tà náà máa rò pé ètò Ọlọ́run ló kọ ọ́. Àmọ́, àwọn arákùnrin olóòótọ́ ò jẹ́ kí lẹ́tà náà tan àwọn jẹ. Wọ́n mọ̀ pé ohun tó wà nínú lẹ́tà yẹn ta ko ohun tí ètò Ọlọ́run kọ́ wọn. Bákan náà lásìkò wa yìí, àwọn ọ̀tá òtítọ́ máa ń lo Íńtánẹ́ẹ̀tì àti ìkànnì àjọlò láti fọ̀rọ̀ ránṣẹ́ kí wọ́n lè dá ìyapa sáàárín wa. Dípò “kí ọkàn [wa] tètè mì,” ó yẹ ká ronú dáadáa nípa ohun tá a gbọ́ tàbí ohun tá a kà bóyá ó ta ko òtítọ́ tá a ti kọ́, ìyẹn sì máa dáàbò bò wá.—2 Tẹs. 2:2; 1 Jòh. 4:1. w24.07 12 ¶14-15
Saturday, April 18
Tí ẹnikẹ́ni bá dẹ́ṣẹ̀, a ní olùrànlọ́wọ́.—1 Jòh. 2:1.
Ìpinnu tó ṣe pàtàkì jù téèyàn lè ṣe ni pé kó ya ara ẹ̀ sí mímọ́ fún Jèhófà, kó sì wà lára àwọn tó ń jọ́sìn ẹ̀. Ohun tí Jèhófà fẹ́ kí gbogbo èèyàn ṣe nìyẹn. Kí nìdí? Ó fẹ́ ká jẹ́ ọ̀rẹ́ òun, ká sì wà láàyè títí láé. (Diu. 30:19, 20; Gál. 6:7, 8) Jèhófà kì í fipá mú ẹnikẹ́ni láti sin òun. Ó gba kálukú wa láyè láti pinnu ohun tá a máa ṣe. Àmọ́, tí Kristẹni kan tó ti ṣèrìbọmi bá rú òfin Ọlọ́run, tó sì dẹ́ṣẹ̀ tó burú jáì ńkọ́? Tẹ́ni náà ò bá ronú pìwà dà, a gbọ́dọ̀ mú un kúrò nínú ìjọ. (1 Kọ́r. 5:13) Síbẹ̀, Jèhófà retí pé kí ẹlẹ́ṣẹ̀ náà ronú pìwà dà kó sì pa dà sọ́dọ̀ òun. Ìdí pàtàkì tí Jèhófà fi pèsè ìràpadà nìyẹn, kí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ tó ronú pìwà dà lè rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà. Torí Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ wa, ó ń fìfẹ́ rọ àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ pé kí wọ́n ronú pìwà dà.—Sek. 1:3; Róòmù 2:4; Jém. 4:8. w24.08 14 ¶1-2