OHUN TÓ O LÈ FI KẸ́KỌ̀Ọ́
Bá A Ṣe Lè Lóye Àwọn Àpèjúwe Inú Bíbélì
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àpèjúwe ló wà nínú Bíbélì. Síbẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn tó ń ka Bíbélì kì í lóye àwọn àpèjúwe yìí. (Mát. 13:13) Kí ló máa jẹ́ kó o lóye àwọn àpèjúwe tó wà nínú Bíbélì? Àwọn àbá yìí máa ràn ẹ́ lọ́wọ́:
Mọ ohun tí àpèjúwe náà dá lé àti àfiwé tí wọ́n lò. Lọ́pọ̀ ìgbà, àpèjúwe kan máa ń ní ohun tó dá lé àti àfiwé tí wọ́n fi gbé kókó ọ̀rọ̀ náà yọ. Bí àpẹẹrẹ, Ìfihàn 3:3 fi ìpadàbọ̀ Jésù wé ìgbà tí olè ń bọ̀. Ìpadàbọ̀ Jésù ni àpèjúwe náà dá lé, àfiwé tó sì lò ní bí olè ṣe máa ń wá.
Ronú nípa bí ohun tí àpèjúwe náà dá lé ṣe jọra pẹ̀lú àfiwé tí wọ́n lò. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, wàá rí ohun tó mú kí méjèèjì jọra.
Ṣèwádìí kó o lè rí ohun tí àpèjúwe náà túmọ̀ sí gan-an. Nígbà míì, ìjọra tó wà láàárín ohun tí àpèjúwe kan dá lé àti àfiwé tí wọ́n lò lè mú kéèyàn ṣi àpèjúwe náà lóye. Nínú àpẹẹrẹ tá a sọ lẹ́ẹ̀kan, kì í ṣe pé Jésù fẹ́ wá jalè ló ṣe ń bọ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, ohun tí àpèjúwe yẹn túmọ̀ sí ni pé, bó ṣe jẹ́ pé èèyàn kì í mọ ìgbà tí olè ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ náà la ò mọ ìgbà tí Jésù ń bọ̀.