OHUN TÓ O LÈ FI KẸ́KỌ̀Ọ́
Múra Ìdáhùn Ẹ Sílẹ̀ Kó O Lè Gbé Àwọn Ará Ró
Láwọn ìpàdé wa, a lè gbé àwọn ará wa ró, ká sì fún wọn níṣìírí tá a bá ń dáhùn. (Héb. 10:24, 25) Báwo la ṣe lè fi ìdáhùn wa gbé àwọn ará ró?
Gbàdúrà sí Jèhófà. Bẹ̀ ẹ́ pé kó jẹ́ kí ìdáhùn ẹ lè yìn ín lógo, kó sì gbé àwọn míì ró.—Sm. 35:18.
Gbìyànjú láti dáhùn lọ́rọ̀ ara ẹ. Tó o bá ń sapá láti dáhùn lọ́rọ̀ ara ẹ, dípò kó o kà á jáde bó ṣe wà nínú ìwé gẹ́lẹ́, ìdáhùn ẹ máa gbé àwọn míì ró.
Jẹ́ kí ìdáhùn ẹ ṣe ṣókí. Ìdáhùn tí ò gùn tí ò sì lọ́jú pọ̀ ló sábà máa ń fún àwọn míì níṣìírí, á sì jẹ́ káwọn náà lè dáhùn nípàdé.—Òwe 10:19.
Má ṣe máa fi ìdáhùn ẹ gún àwọn èèyàn lára. Kò yẹ kó o máa fi ìdáhùn ẹ bá àwọn ará wí tàbí kó o máa fi ṣàríwísí wọn.
Tí wọn ò bá tiẹ̀ pè ẹ́ láti dáhùn, o ṣì lè fún àwọn ará níṣìírí tó o bá ń fetí sílẹ̀ dáadáa, tó o sì ń gbóríyìn fáwọn tó dáhùn.—Òwe 10:21.