ÀWỌN TÍ BÍBÉLÌ SỌ̀RỌ̀ WỌN
Ọbadáyà Bẹ̀rù Ọlọ́run
Ọbadáyà ló ń bójú tó agboolé Ọba Áhábù. Áhábù burú gan-an, ó sì gbà káwọn èèyàn máa jọ́sìn Báálì nílẹ̀ Ísírẹ́lì. Àmọ́, Ọbadáyà bẹ̀rù Jèhófà “láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.” (1 Ọba 18:1-13) Torí náà nígbà tí Ayaba Jésíbẹ́lì pàṣẹ pé kí wọ́n pa gbogbo wòlíì Jèhófà, Ọbadáyà mọ̀ pé òun gbọ́dọ̀ nígboyà kóun lè dáàbò bò wọ́n. Nígbà yẹn, téèyàn bá fi wòlíì kan péré pa mọ́ wàhálà ni, àmọ́ Ọbadáyà kó ọgọ́rùn-ún wòlíì pa mọ́, ó sì ń fún wọn lóúnjẹ lásìkò tí ìyàn mú! Fojú inú wo bó ṣe máa nira tó láti fi àwọn wòlíì yẹn pa mọ́, kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn wòlíì èké tó ń bá ọba àti ayaba ṣiṣẹ́ má sì mọ̀.—1 Ọba 18:19.
Kí la lè kọ́ lára ọkùnrin tó bẹ̀rù Ọlọ́run yìí? Òótọ́ ni pé Ọbadáyà bẹ̀rù Áhábù, àmọ́ ó bẹ̀rù Ọlọ́run ju Áhábù lọ. Ìyẹn ló jẹ́ kó nígboyà, kó sì fẹ̀mí ẹ̀ wewu kó lè dáàbò bo àwọn èèyàn Ọlọ́run. Táwọn aláṣẹ bá fòfin de iṣẹ́ wa níbi tá à ń gbé, ìbẹ̀rù Ọlọ́run máa ran àwa náà lọ́wọ́. Tá a bá bẹ̀rù Ọlọ́run, ẹ̀rù ò ní bà wá láti dúró ti àwọn ará wa tó níṣòro, àá sì lè ràn wọ́n lọ́wọ́.