Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Nígbà tí Hánà ń gbàdúrà, ó lo àwọn ọ̀rọ̀ tó jọ ọ̀rọ̀ tí Mósè kọ. Ìyẹn fi hàn pé ó wáyè láti ronú dáadáa nípa ohun tó wà nínú Ìwé Mímọ́. (Diu. 4:35; 8:18; 32:4, 39; 1 Sám. 2:2, 6, 7) Ọ̀pọ̀ ọdún lẹ́yìn náà, nígbà tí Màríà ìyá Jésù ń yin Ọlọ́run, ó lo ọ̀rọ̀ tó jọ èyí tí Hánà sọ.—Lúùkù 1:46-55.