Kò Jẹ́ Kí Wọ́n Gbé Owó Ọkùnrin náà Lọ
Nígbà tí ọkùnrin kan ń wọkọ̀ láti ìlú kan lọ sí òmíràn láàárín Nàìjíríà, ní Ìwọ̀ Oòrùn Áfíríkà, ó bá ọkùnrin kan tí wọ́n jọ wọkọ̀ sọ̀rọ̀ nípa “Àwọn Àṣà Tí Ọlọ́run Kórìíra,” ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ kan tí ó wà nínú ìwé pẹlẹbẹ Kí Ni Ọlọrun Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa? Nígbà tí ọkọ̀ náà dúró nílé àrójẹ kan, ọkùnrin tí ìwé pẹlẹbẹ náà ti wọ̀ lọ́kàn yìí gbé àpò kan tó gbé dání síta, ó sì ṣàlàyé pé: “Owó ló wà nínú rẹ̀. . . . Inú àpò ọ̀kan lára àwọn èrò ọkọ̀, tó wà níbi ìkẹ́rùsí, ni mo ti jí i gbé.”
Àmọ́, ọkùnrin tó jí owó náà ti wá kábàámọ̀ ohun tó ṣe, ó sì fẹ́ dá owó náà padà fún ẹni tó ni í. Ọ̀dọ́mọkùnrin oníṣòwò kan, tí òun náà wà nínú ọkọ̀ kan náà sọ pé tòun ni àpò náà. Ọ̀kẹ́ méje ààbọ̀ [150,000] náírà (nǹkan bí ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán dọ́là) ló wà níbẹ̀. Olè tó ti ń tẹ̀ lé ẹni tó lowó náà fún nǹkan bí ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta [500] kìlómítà, wí fún oníṣòwò náà pé kí ó dúpẹ́ lọ́wọ́ ẹni tó bá òun jíròrò ohun tó wà nínú ìwé pẹlẹbẹ náà. Ó ṣàlàyé pé, ohun tí òun gbọ́ yẹn ló mú kí òun dá owó náà padà.
Nígbà tí awakọ̀ àti àwọn èrò ọkọ̀ yòókù gbọ́ ohun tó ṣẹlẹ̀, ó yà wọ́n lẹ́nu gan-an, gbogbo wọn sì béèrè fún ẹ̀dà ìwé pẹlẹbẹ náà. Oníṣòwò náà kì í jẹ́ kí Àwọn Ẹlẹ́rìí bá òun sọ̀rọ̀ tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ó wá fẹ́ kí wọ́n máa bá òun ṣèkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nísinsìnyí.
O lè rí ìsọfúnni nípa bí o ṣe lè rí ìwé pẹlẹbẹ olójú-ewé méjìlélọ́gbọ̀n tó ṣeyebíye yìí gbà nípa kíkọ̀wé kún fọ́ọ̀mù tó wà nísàlẹ̀ yìí, kí o sì fi ránṣẹ́ sí àdírẹ́sì tí a kọ sínú fọ́ọ̀mù náà tàbí sí àdírẹ́sì tó ṣe wẹ́kú lára àwọn tí a tò sí ojú ìwé karùn-ún ìwé ìròyìn yìí.
□ Ẹ fi ìsọfúnni ránṣẹ́ sí mi nípa bí mo ṣe lè rí ìwé pẹlẹbẹ náà, Kí Ni Ọlọrun Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?, gbà.
Kọ èdè tí o fẹ́
□ Ẹ jọ̀wọ́, ẹ kàn sí mi nípa ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé lọ́fẹ̀ẹ́.